Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ǹjẹ́ Ipò Òṣì Lè Dópin Jáé?

Ǹjẹ́ Ipò Òṣì Lè Dópin Jáé?

Ǹjẹ́ Ipò Òṣì Lè Dópin Jáé?

SÓLÓMỌ́NÌ ọlọ́gbọ́n Ọba Ísírẹ́lì ìgbàanì sọ pé: “Sì wò ó! omijé àwọn tí a ń ni lára, ṣùgbọ́n wọn kò ní olùtùnú; ọ̀dọ̀ àwọn tí ń ni wọ́n lára sì ni agbára wà, tí ó fi jẹ́ pé wọn kò ní olùtùnú.” (Oníwàásù 4:1) Ó dájú pé ọ̀pọ̀ lára àwọn tí ó sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ pé à ń ni lára wọ̀nyí ló jẹ́ òtòṣì bákan náà.

A ò lè fi kìkì ọ̀ràn owó díwọ̀n ipò òṣì. Gẹ́gẹ́ bó ṣe wà nínú ìsọfúnni oníṣirò tí Báńkì Àgbáyé gbé jáde ní June 2002, “wọ́n fojú bù ú pé lọ́dún 1998, owó tí àwọn èèyàn lágbàáyé tí iye wọn lé ní bílíọ̀nù kan ń ná lẹ́nì kọ̀ọ̀kan lójúmọ́ kò tó dọ́là kan . . . nígbà tí iye èèyàn tó kù díẹ̀ kó pé bílíọ̀nù mẹ́ta ń ná iye tó dín sí dọ́là méjì lójúmọ́.” Wọ́n sọ pé lóòótọ́ ni iye yẹn kéré sí iye tí wọ́n ti fojú bù tẹ́lẹ̀, “àmọ́ iye yìí ṣì ga jù tá a bá ń sọ nípa àwọn èèyàn tí ń jìyà nítorí ipò òṣì.”

Ǹjẹ́ ipò òṣì lè dópin láé? Jésù Kristi sọ fáwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé: “Ẹ̀yin ní àwọn òtòṣì nígbà gbogbo pẹ̀lú yín.” (Jòhánù 12:8) Ṣé èyí wá túmọ̀ sí pé ipò òṣì àti gbogbo wàhálà tó ń fà kò ní dópin láé ni? Rárá o, òótọ́ ni pé Jésù ò ṣèlérí fáwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé gbogbo wọn ló máa lówó bíi ṣẹ̀kẹ̀rẹ̀, síbẹ̀ a ò gbọ́dọ̀ wá torí ohun tó sọ yìí gbà pé kò sọ́nà àbáyọ fáwọn òtòṣì.

Pẹ̀lú bí gbogbo ìsapá ẹ̀dá èèyàn àti gbogbo ìlérí tí wọ́n ń ṣe pé àwọn á mú ipò òṣì kúrò ṣe já sí pàbó, Bíbélì tí í ṣe Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run fi dá wa lójú pé kò ní sí ipò òṣì mọ́ láìpẹ́. Kódà, Jésù polongo “ìhìn rere fún àwọn òtòṣì.” (Lúùkù 4:18) Ìhìn rere yìí ní nínú ìlérí náà pé ipò òṣì máa tó di ohun àtijọ́. Èyí á ṣẹlẹ̀ nígbà tí Ìjọba Ọlọ́run bá mú ipò àwọn nǹkan padà sí bó ṣe yẹ lórí ilẹ̀ ayé.

Ayé á mà yàtọ̀ gan-an nígbà náà o! Jésù Kristi Ọba tí ń bẹ lọ́run “yóò káàánú ẹni rírẹlẹ̀ àti òtòṣì, yóò sì gba ọkàn àwọn òtòṣì là.” Àní, “yóò tún ọkàn wọn rà padà lọ́wọ́ ìnilára àti lọ́wọ́ ìwà ipá.” —Sáàmù 72:13, 14.

Míkà 4:4 sọ nípa àkókò yẹn pé: “Wọn yóò sì jókòó ní ti tòótọ́, olúkúlùkù lábẹ́ àjàrà rẹ̀ àti lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀, kì yóò sì sí ẹnì kankan tí yóò máa mú wọn wárìrì; nítorí ẹnu Jèhófà àwọn ẹgbẹ́ ọmọ ogun ti sọ ọ́.” Ìjọba Ọlọ́run á mú gbogbo ìṣòro tó ń bá ẹ̀dá èèyàn fínra kúrò, kódà ó máa mú àìsàn àti ikú pàápàá kúrò. Ọlọ́run “yóò gbé ikú mì títí láé, dájúdájú, Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ yóò nu omijé kúrò ní ojú gbogbo ènìyàn.”—Aísáyà 25:8.

O lè gbẹ́kẹ̀ lé àwọn ìlérí yìí nítorí pé Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ló sọ ọ́. O ò ṣe kúkú fúnra rẹ ṣàyẹ̀wò àwọn ẹ̀rí tó fi hàn pé àwọn àsọtẹ́lẹ̀ inú Bíbélì ṣe é gbẹ́kẹ̀ lé?

[Àwòrán Credit Line tó wà ní ojú ìwé 32]

Fọ́tò FAO/M. Marzot